The Democratic Republic of the Yoruba Official Information Portal

Olódùmarè, Ẹlẹ́da Ọmọ Yorùbá àti Olùṣẹ̀dá Ilẹ̀ Yorùbá, olùṣẹ̀dá àwọn babanlá baba wa, Ẹni tí Òun Fún’ra rẹ̀ jíìnkí ilẹ̀ Yorùbá pẹ̀lú agbára ẹ̀mí, agbára Ìṣẹ̀dálẹ̀, Agbára Ìwòsàn, àti bẹ́ẹ̀-bẹ́ẹ̀ lọ, ni ó fi oríṣiríṣi iìnkan àti Agbára wọ̀nyí ṣe Yorùbá àti Ilẹ̀ Yorùbá lọ́jọ̀, pé kí a máa lò wọ́n fún ìgbélékè ìgbésí ayé wa; lọ́nà kíní, kí ẹ̀mí wa, ẹ̀mí ọmọ Yorùbá ó lè jogún irúfẹ́ agbára tí Èdùmàrè fúnra Rẹ̀ ti fi sí ilẹ̀ àti àyíká àti òfúrufú wa, kí á le jẹ́ ẹ̀yà tí yíò máa máa wà títí, nítorí Àkọ́dá Elédùmarè ni a jẹ́, Ẹni ti Olódùmarè fúnra Rẹ̀ jogún Agbára Rẹ̀ fún; pé kí àwa Yorùbá, nínú Ọlánlá àti ipò gíga tí òun Ẹlẹ́da fi ‘wa sí, nínú ayé yí, kí á le fi Agbára, Ìmọ̀, pẹ̀lú Ògo Yí ṣe Àkóso Ayé yí fún òun.

Ìdí ni’yí tí ó fi fún wa ní Ilẹ̀ àti Àyíká tí ó lógo, tí ó kún fún Ìmọ̀, pé kí àwa ọmọ Yorùbá ó lè máa Túmọ̀ Àyíka wa yí, láti lè mọ Òun Ẹlẹ́da wa si: ìbá ṣeé pé a ti tètè kọ’bi ara sí èyí ni, àwa ni Èdùmàrè jogún àkóso Àgbáyé fún, ní Rere!

Olódùmarè, jọ̀wọ́ dárí Ẹ̀ṣẹ̀ wa yí Jì wá! Kí ó ṣí ojú wa sí Ìtúmọ̀ àyíká wa, kí á le rí Ògo Rẹ, àti Ọ̀rọ̀ Rẹ, tí ìwọ nsọ sí wa, lójoojúmọ́, kí Ọ̀rọ̀ yí lè ṣe Ìtọ́nà fún wa, bí O ṣe nsọọ́ sí wa, láti igi wa, láti Omi wa, láti àjà inú Ilẹ̀ wa, bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, nítorí ìwọ ni Alágbára, o sì gbé Agbára yí Lé Yorùbá lọ́wọ́, ká fi ṣe Àkóso Ayé yí fún Ọ, ìwọ Olódùmarè.

Jọ̀wọ́, bá wa ṣíjú wo ọ̀rọ̀ Rẹ, àti Ògo Rẹ, tí O ti kọ, tí O sì fi sí inú Omi Àjàbọ́ ti Ẹ̀rìn-Ìjèṣà; máṣe jẹ́ kí Omi yí kí ó kígbe kú!

Ojojúmọ́ ni Ó nkígbe, tí Ó sì npè wá, pé Kí á bojú wo Òun; òun nbá wa sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n a ò fetí sí ohun tí òun nsọ; Olódùmarè, jọ̀wọ́ má ṣe jẹ́ kí Omi Àjàbọ́ Ẹ̀rìn-Ìjèṣa kí ó bínú sí wa mọ́: a mọ̀ pé Angẹ́lì Rẹ, ìkan nínú àwọn Ángẹ́lì tí Ìwọ Olódùmarè sọ L’ọjọ̀ ni, sí ilẹ̀ Yorùbá, pé, tí a bá ti nri, kí Ìmọ̀ kí Ó máa sọ nínú wa; kí òye àyíká wa, kí Ó máa sọ, kí ó di Ìwòsàn fún wa; kí Ìgbàlà ní Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ Ó lè jẹ́ àjogún Ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá, kí ilẹ̀ Orílẹ̀-Èdè wa, Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá, ó le jẹ́ Odi Agbára yí wa ká; kí Ọ̀tá kankan má ṣe lè borí wa, ṣùgbọ́n kí Àwọn Ọmọ Wa, láti Ìran-dí-‘Ran, ó le jogún ayé yí; kí wọ́n dúró gẹ́gẹ́bí Ìmọ́lẹ̀ Olódúmarè; kí ayé ó rí Wọn, kí ayé sì máa júbà ìwọ Ọlọ́run Ọ̀gá-Ogo, nítorí wọ́n ṣe àbápàdé Ògo Rẹ̀ nínú Ẹ̀yà náà tí ìwọ ti Yàn, Ẹ̀ya Ìran Ọmọ Yorùbá.

Democratic republic of the Yoruba ominira new update | Yoruba Nation | Newest Nation in Africa, Youngest country in the World 2024 . Erin Ijesa Water Fall News update
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!

Ní àìpẹ́ yí ní a rí fọ́nrán tí ó fi hàn, bí àwọn ẹ̀dá ọmọ ènìyàn ṣé kó ìdọ̀tí wọn sí Ẹ̀bá Omi-Àjàbọ́ Ológo yí: ó ṣe’ni láanú, ó ti’ni lójú, ó gba ẹkún lójú ojúlówó ọmọ-ìbílẹ̀ Yorùbá, pé, ìkan nínú àwọn pàtàkì Angẹ́lì Oódùmarè sí Ìran Yorùbá ni wọ́n ṣe irú ìdọ̀tí báyi lé lórí!

Èdùmàrè, jọ̀wọ́, ṣílẹ̀kùn Àyọ̀ fún Ìjọba-Adelé wa, láìpẹ́; kí o fi Àánú rẹ Ṣí’dí ọ̀tá wa, Nàìjíríà, kúrò ní ilẹ̀ Wa, kí á le Rí Ojú-Rere rẹ, nígbàtí Ìjọba-Adelé wa bá wọnú àwọn ilé-iṣẹ́ wa gbogbo lọ, láti ṣe Àkóso ilẹ̀ Yorùbá; inú wa kí ó Dùn, tí A Ó sì máa kọrin Ogo Rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn Angẹ́lì tí o fi yí wa ká wọ̀nyí, bí Omi-Àjàbọ́ Ẹ̀rìn-Ìjèṣà, yíò fò fáyọ̀, pé, Ìgbàlà Ọmọ Yorùbá ti dé: wọn ó sì fọhùn sí wa: Ìran Ọmọ Aladé yíò sì gbọ́ Ọ̀rọ̀ Rẹ Nínú Ohùn wọn: Ẹ̀mí yíò kan Ẹ̀mí, a ó sì máa yìn ọ́ títí Ayé, ṣebí O ti sọ̀ọ́ pé ìfarahàn Rẹ wà nínú àwọn ohun tí o dá; Olùgbàlà tí O dẹ̀ rán sí’wa, Ìránṣẹ Rẹ, Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá, ti sọ fún wa pé, Ohun gbogbo tí ìwọ Olódùmarè dá, ni ó ní Ẹ̀mí tirẹ̀: Omi-Àjàbọ́, Ẹ̀rìn-Ìjèṣa, Fọ’hùn sí wa, ní Orúkọ Olódùmarè, kí Inú Ọmọ Yorùbá Ó dùn, kí àwọn Ọ̀tá ó ṣègbé.